ÌRÒYÌN: Àwọn Ajínigbé tún jí èèyàn mọ́kànlá gbé ní Isapa, lẹ́bà ìlú Eruku, wọ́n yin ìyá arúgbó ní ìbọn


Egbirin ọtẹ, bi a se n pa ọkan, ni ominran n ru ni ẹka eto aabo ni ipinlẹ Kwara ati ilẹ Naijiria lapapọ.

Idi ni pe iroyin miran to tun n tẹ wa lọwọ, ti akọroyin wa si ti fidi rẹ mulẹ ni pe awọn ajínigbé tun ti ya wọ ìlú Ìsàpà nipinlẹ Kwara, ti wọ́n si jí èèyàn mọ́kànlá gbé lọ.

Akọtun isẹlẹ ijinigbe yii si lo n waye lẹyin wakati merinlelogun tawọn agbebọn yọnda awọn olujọsin mejidinlogoji ti wọn ji gbe ni ilu Eruku nijọba ibilẹ Ekiti ipinlẹ Kwara.

Ilu Isapa yii si lo wa ni ijọba ibilẹ Ekiti bakan naa, to si tun sun mọ ilu Eruku.

Awọn ajinigbe naa, ti wọn ji eeyan mọkanla gbe ni ilu naa, tun yinbọn mọ iya agbalagba kan.

Gẹgẹ bi ẹni ti isẹlẹ naa soju rẹ, to ba akọroyin BBC News Yorùbá sọrọ se wi, deedee aago meje asalẹ ọjọ Aje ana ni isẹlẹ naa waye nilu Isapa.

Ọgbẹni kayọde fidi iṣẹlẹ yii mulẹ ọdẹ ibilẹ kan lo kọkọ lọ koju awọn agbebọn naa, ti wọn si yinbọn lu, sugbọn ibọn naa kọ wọle si lara .

Lẹyin eyi, Kayode ni wọn kọlu awọn araalu, ti wọn si yinbọn mọ iya agbalagba lẹyin eyi, wọn ji eeyan mọkanla gbe.

"Hausa mẹwa lọkunrin ati obinrin pẹlu alaboyun kan to jẹ ẹya Yoruba ni wọn ji gbe.

O salaye pe inu ibẹru bojo lawọn eeyan agbegbe naa wa lati ana, ti ko si ti si igbesẹ kankan lori ẹ.

O fi diẹ mulẹ pe, awon mẹta ninu awọn mọkanla naa ti mori bọ lọwọ awọn ajinigbe naa, ti wọn si wa ni ilu Eruku bayii.

— BBC Yoruba

Comments

Popular posts from this blog

WAEC Announces Job Vacancies (Apply Now)

APPLY: Nigerian Army Announces 2026 Recruitment Exercise For Short Service Intake

BREAKING: State Government Declares Tuesday Public Holiday for Teachers’ Celebration